News

Àwọn ajínigbé yọ̀ǹda ìbejì Akeugbagold

Fẹ́mi Akínṣọlá

Ṣé yorùbá bọ̀ wọ́n ní kò sí ohun tó le tí kìí dẹ̀rọ̀.N tó sì sókùkùn lójú ẹ̀dà hàn gbangba níwájú Adẹ́dàá.

Lẹ́yìn ọjọ mẹ́jọ tí ìṣẹ̀lẹ̀ ajániláyà pàtì lórí bí wọ́n se jí ọmọ oníwáàsí àgbà  Alhaji Taofeeq Akewugbagold gbé, ó ní  àwọn ìbejì òun náà tí di rírí padà .

Ọ̀rọ̀ yìí ló fí léde lójú òpó fesibúùkù rẹ̀.
Bí a o bá gbàgbé, ìṣẹ̀lẹ̀ náà tí n pé ọsẹ kàn báyìí tí ìròyìn ti kọkọ tàn mọ́ lẹ sí bí wọ́n se jí àwọn ìbejì náà gbé.
Ó kọọ báyìí s’órí itàkùn fesibúùkù rẹ̀

“ALHAMDULILLAH! Ní 5.30 Àárọ Àìkú ọjọ́ kẹta oṣù Karùn ún  wọ́n dá àwọn ọmọ ọ̀ mi tí wọ́n jígbé padà fúnmi létí igbó kan, lẹ́yìn tí wọ́n tí ló  ọsẹ kan lẹ́yìn ìṣẹ̀lẹ̀ náà.Mo dúpẹ́ lọ́wọ́ gbogbo yín fún àdúrà àti àdúrótì yín lásìkò Ìlàkàkà mì láti rí àwọn ìbejì mi ti wọ́n jígbé náà.  JAZAKUMULLAHU KHAIRAN. ABERE MI BO SINU OKUN, OLOUN YO PADA FUN MI.“

Ṣùgbọ́n  Sheik náà kò ṣọ bóyá àwọn ajínigbé náà padà gba owó ìtúsílẹ̀ tí wọ́n kọkọ bèèrè lọ́wọ́ ọ́ rẹ̀.

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *